Lẹyin ọpọ oṣu ti ipolongo ibo fi wa’ye, eto idibo pada tẹle l’ana ode yii ọjọ kẹẹdogun oṣu kẹjọ ọdun 2026 ni’pinlẹ Ọṣun, kinni naa le pupọ de’bi pe ibo ipinlẹ Ọṣun nikan mi gbogbo orilẹ-ede Naijiria titi.
Lopin ohun gbogbo, ka-wi-ka-fọ, ka-fọ-ka-wi, ajọ INEC kede esi idibo ipinlẹ Ọsun ni kutuhai oni, ọjọ Aiku (Sunday) ọjọ kẹrindilogun oṣu kẹjọ ọdun 2026 ni nnkan aago meje aabọ owurọ ku iṣẹju perete.
Nibamu pẹlu ikede Giwa fasiti Oyẹ Ekiti, Ọjọgbọn Joshua Oguwọle, ẹni to wa ni’po lati kede esi ibo naa, o ṣalaye pe lẹyin apapọ akojọpọ gbogbo ibo, Gomina Ademọla Adeleke Jackson ti inu ẹgbẹ oṣelu Accord lo gbe igba oroke, to si wọ’le idibo naa pẹlu ibo to le belenja ni ẹgbẹrun l’ọna ẹẹdẹgbẹta (511,067), ti Ogunwolẹ si da Adeleke pada gẹgẹ bii olubori Oludije, to ja si saa keji Gomina Adeleke l’Ọṣun.
Ijọba ibilẹ mọkandinlogun (19) ninu ọgbọn (30) Adeleke ti bori, Ariwa Ẹdẹ, Guusu Ẹdẹ, Ejigbo, Iwo, Ẹgbẹdọrẹ, Ariwa Ifẹ, Ila-oorun Ifẹ, Aaringbungbun Ifẹ, Oriade, Ifẹlodun, Orolu, Ayedaade, Ayedire, Odo Ọtin, Boluwaduro, Iwọoorun Ileṣa, Ifẹdayo, Oṣogbo ati Ayedire.